Mátíù 15:24-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Ó dáhùn pé, “Àgùntàn ilẹ̀ Ísírẹ́lì tí ó nù nìkan ni a rán mi sí”

25. Obìnrin náà wá, ó wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó bẹ̀bẹ̀ sí i pé, “Olúwa ṣàánú fún mi.”

26. Ó sì dáhùn wí pé, “Kò tọ́ kí a gbé oúnjẹ àwọn ọmọ fún àwọn ajá.”

27. Obìnrin náà sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, síbẹ̀síbẹ̀ àwọn ajá a máa jẹ èérún tí ó ti orí tábìlì olówó wọn bọ́ sílẹ̀.”

Mátíù 15