5. Ṣùgbọ́n Jésù kò da lohùn síbẹ̀, tóbẹ́ẹ̀ ti ẹnu fi ya Pílátù.
6. Ní báyìí, nígbà àjọ, gẹ́gẹ́ bí àsà, òun a máa dá òǹdè kan sílẹ̀ fún àwọn, ẹnikẹ́ni tí wọ́n bá béèrè fún.
7. Ọkùnrin kan wà tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Bárábà. Wọ́n ti ju òun àti àwọn ọlọ̀tẹ̀ ẹgbẹ́ rẹ̀ sí ọgbà ẹ̀wọ̀n, nítorí wọ́n sọ̀tẹ̀ sí ìjọba, wọ́n sì pa ènìyàn nínú ìdìtẹ̀ wọn.
8. Ọ̀pọ̀ ènìyàn sì lọ bá Pílátù, wọ́n ní kí ó ṣe bí ó ti máa ń ṣe fún wọn ní ọdọọdún.
9. Pílátù béèrè lọ́wọ́ wọn wí pé, “Ṣe ẹ̀yín ń fẹ́ kí èmi dá ọba àwọn Júù sílẹ̀ fún yin?”