Lúùkù 23:4-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Pílátù sì wí fún àwọn Olórí àlùfáà àti fún ìjọ ènìyàn pé, “Èmi kò rí ẹ̀ṣẹ̀ lọ́wọ́ Ọkùnrin yìí.”

5. Wọ́n sì túbọ̀ tẹnumọ́ ọn pé, “Ó ń ru ènìyàn sókè, ó ń kọ́ni káàkiri gbogbo Jùdéà, ó bẹ̀rẹ̀ láti Gálílì títí ó fi dé ìhínyìí!”

6. Nígbà tí Pílátù gbọ́ orúkọ Gálílì, ó béèrè bí ọkùnrin náà bá jẹ́ ará Gálílì.

Lúùkù 23