Léfítíkù 26:36-40 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

36. “ ‘Èmi yóò jẹ́ kí ó burú fún àwọn tí ó wà ní ilẹ̀ ìgbékùn débi pé ìró ewé tí ń mì lásán yóò máa lé wọn sá. Ẹ ó máa sáré bí ìgbà tí wọ́n ń lé yín lójú ogun. Ẹ ó sì subú láìsí ọ̀ta láyìíká yín

37. Wọn yóò máa subú lu ara wọn, bí ẹni tí ń sá fún ogun nígbà tí kò sí ẹni tí ń lé yín. Ẹ̀yin kì yóò sì ní agbára láti dúró níwájú ọ̀ta yín.

38. Ẹ̀yin yóò ṣègbé láàrin àwọn orílẹ̀ èdè abọ̀rìṣà. Ilẹ̀ ọ̀ta yín yóò sì jẹ yín run.

39. Àwọn tí ó ṣẹ́kù nínú yín ni yóò sòfò dànù ní ilẹ̀ ọ̀ta yín torí ẹ̀ṣẹ̀ yín àti ti àwọn babańlá yín.

40. “ ‘Bí wọ́n bá jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn àti ti babańlá wọn, ìwà ìṣọ̀tẹ̀ wọn àti bí wọ́n ti ṣe lòdì sí mi.

Léfítíkù 26