Léfítíkù 14:31-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

31. Ọ̀kan fún ẹbọ ẹṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ ẹ̀bi pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ: Àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù níwájú Olúwa ní ìpò ẹni tí a fẹ́ wẹ̀ mọ́.”

32. Òfin nìyí fún ẹnikẹ́ni tí ó bá ní àrùn ara tí ó le ran tí kò sì lágbára láti rú ẹbọ tí ó yẹ fún ìwẹ̀nùmọ́ bí a ti fi lélẹ̀.

33. Olúwa sọ fún Mósè àti Árónì pé.

34. “Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ Kénánì tí mo fi fún yín ni ìní, tí mo sì fí àrùn ẹ̀tẹ̀ sínú ile kan ní ilẹ̀ ìní yín.

35. Kí ẹni tí ó ní ilọ̀ náà lọ sọ fún àlùfáà pé, ‘Èmi tí rí ohun tí ó jọ àrùn ẹ̀tẹ̀ ní ilé mi.’

36. Àlùfáà yóò pàṣẹ kí ẹnikẹ́ni tàbí ohunkóhun má ṣe wà nínú ilé náà, kí ó tó lọ yẹ ẹ̀tẹ̀ náà wò, kí ohunkóhun nínú ilé náà má báà di àìmọ́. Lẹ́yìn èyí àlùfáà yóò wọlé lọ láti yẹ ilé náà wò.

Léfítíkù 14