Kólósè 2:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Mo fẹ́ kí ẹ mọ bí mo ti ń jìjàkadì fún un yín àti fún àwọn ará Laodékíà àti fún ọ̀pọ̀ ènìyàn mìíràn tí wọn kò ì tí ì rí mi sójú rí.

2. Ohun tí mo ń béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run fún un yín nínú àdúrà mi ni pé, kí a lè mú yín lọ́kàn le, kí a sì lè so yín pọ̀ pẹ̀lú ìfẹ́ to lágbára, kí ẹ lè ní ìjìnlẹ̀ ìrírí ìmọ́ Kírísítì pẹ̀lú òye àti ìmọ̀ tó dájú ṣáká. Nítorí nísinsinyìí, Ọlọ́run ti fi àṣírí ètò hàn. Ìjìnlẹ̀ àṣírí ètò náà ni Kírísítì fúnrarẹ̀.

3. Nínú ẹni tí a fi gbogbo ìsùra ìjìnlẹ̀ ọgbọ́n àti ìmọ̀ pamọ́ sí.

Kólósè 2