9. Láti ara ẹ̀yà Júdà àti ẹ̀yà Síméónì ni wọ́n ti pín àwọn ìlú tí a dárúkọ wọ̀nyí,
10. (Ilú wọ̀nyí ni a fún àwọn ọmọ Árónì tí ó jẹ́ ọ̀kan nínú ìdílé Kóhátì tí í ṣe ọmọ Léfì, nítorí tí ìpín àkọ́kọ́ jẹ́ ti wọn).
11. “Wọ́n fún wọn ní Kiriati Áríbà (tí í ṣe, Hébúrónì), pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù tí ó yí wọn ká, ní ilẹ̀ òkè Júdà. (Áríbà ni baba ńlá Ánákì.)
12. Ṣùgbọ́n àwọn oko àti àwọn abúlé ní agbégbé ìlú náà ni wọ́n ti fi fún Kélẹ́bù ọmọ Jéfúnè gẹ́gẹ́ bí ohun ìní rẹ̀.
13. Ní àfikún wọ́n sì fún àwọn ọmọ Árónì tí í ṣe àlùfáà ní Hébúrónì (ọ̀kannínú ìlú ààbò fún àwọn apàníyàn) pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù rẹ̀, Líbínà,