Jóṣúà 18:20-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Odò Jọ́dánì sí jẹ́ ààlà ní ìhà ìlà-oòrùn.Ìwọ̀nyí ní àwọn ààlà ti ó ṣàmì sí ìní àwọn ìdílé Bẹ́ńjámínì ní gbogbo àwọn àyíká wọn.

21. Ẹyà Bẹ́ńjámínì ní agbo ilé, agbo ilé ni àwọn ìlú wọ̀nyí:Jẹ́ríkò, Bẹti-Hógílà, Emeki-Késísì,

22. Bẹti-Árábà, Sẹ́máráímù, Bẹ́tẹ́lì,

23. Áfímù, Párà, Ófírà

24. Kẹ́fárì, Ámónì, Ófínì àti Gébà, àwọn ìlú méjìlá àti ìletò wọn.

25. Gíbíónì, Rámà, Béérótì,

26. Mísípà, Kéfírà, Mósà,

27. Rẹ́kẹ́mù, Írípẹ́ẹ́lì, Tárálà,

28. Sélà, Háléfì, ìlú Jébúsì (tí íse Jérúsálẹ́mù), Gíbíà àti Kíríátì, àwọn ìlú mẹ́rìnlá àti ìletò wọn.Èyí ni ìní Bẹ́ńjámínì fún ìdílé rẹ̀.

Jóṣúà 18