Jóṣúà 17:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èyí ní ìpín ẹ̀yà Mànásè tí í ṣe àkọ́bí Jósẹ́fù, fún Mákírì, àkọ́bí Mánásè. Mákírì sì ni babańlá àwọn ọmọ Gílíádì, tí ó ti gba Gílíádì àti Básánì nítorí pé àwọn ọmọ Mákírì jẹ́ jagunjagun ńlá.

2. Nítorí náà ìpín yìí wà fún ìyókù àwọn ènìyàn Mánásè: ní agbo ilé Ábíésérì, Hélékì, Ásíríélì, Sékémù, Héférì àti Ṣémídà. Ìwọ̀nyí ní àwọn ọmọ ọkùnrin Mánásè ọmọ Jósẹ́fù ní agbo ilé wọn.

3. Nísinsìn yìí Sẹloféádì ọmọ Héférì, ọmọ Gílíádì, ọmọ Mákírì, ọmọ Mánásè, kò ní ọmọkùnrin, bí kò se àwọn ọmọbìnrin, tí orúkọ wọn jẹ́: Málà, Nóà, Hógílà, Mílíkà àti Tásà.

4. Wọ́n sì lọ bá Élíásárì àlùfáà, Jóṣúà ọmọ Núnì, àti àwọn olórí wí pé, “Olúwa pàṣẹ fún Mósè láti fún wa ní ìní ní àárin àwọn arákùnrin wa.” Bẹ́ẹ̀ ni Jóṣúà fún wọn ní ìní pẹ̀lú àwọn arákùnrin baba wọn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa.

Jóṣúà 17