11. “Nítorí náà èmi kì yóò pa ẹnu mi mọ́,èmi yóò máa sọ nínú ìrora ọkàn mi,èmí yóò máa ṣe ìráhùn nínú kíkorò ọkàn mi.
12. Èmi a máa ṣe ejò òkun tàbí erinmi,tí ìwọ fi ń yan olùṣọ́ tì mi?
13. Nígbà tí mo wí pé, ibùsùn mi yóò tù mí lára,ìtẹ́ mi yóò gbé ẹrù ìráhùn mi pẹ̀lú.
14. Nígbà náà ni ìwọ fi àlá da ẹ̀gbọ̀n bò mi,ìwọ sì fi ìran òru dẹ́rù bà mí.
15. Bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mí yàn láti soàti ikú ju kí ń wà láàyè ní ipò tí ara mí wà yìí lọ.
16. O ṣú mi, èmi kò le wà títí:jọ̀wọ́ mi jẹ́, nítorí pé asán ni ọjọ́ mi.