Jóòbù 17:3-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. “Ǹjẹ́ nísinsínyí, fi lélẹ̀ yàn onígbọ̀wọ́fún mi lọ́dọ̀ rẹ; ta ni Olúwa tí yóò le ṣe ààbò fún mi?

4. Nítorí pé ìwọ ti ṣé wọ́n láyà kúrònínú òyè; nítorí náà ìwọ kì yóò gbé wọn lékè.

5. Ẹni tí ó fi àwọn ọ̀rẹ́ hàn fúnìgárá, òun ni ojú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò mú òfo.

6. “Ọlọ́run ti sọ mi di ẹni òwe fúnàwọn ènìyàn; níwájú wọn ni mo dàbí ẹni ìtutọ́ sí ní ojú.

7. Ojú mí ṣú bàìbàì nítorí ìbìnújẹ́,gbogbo ẹ̀yà ara mi sì dàbí òjìji.

8. Àwọn olódodo yóò yanu sí èyí,ẹni aláìsẹ̀ sì bínú sí àwọn àgàbàgebè.

9. Olódodo pẹ̀lú yóò di ọ̀nà rẹ̀ mú,àti ọlọ́wọ́ mímì yóò máa lera síwájú.

10. “Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti gbogbo yín, ẹ yípadà, kí ẹ sì tún bọ̀ nísinsin yìí;èmi kò le rí ọlọgbọ́n kan nínú yín.

11. Ọjọ́ tí èmi ti kọjá, ìro mi ti fàjá, àní ìro ọkàn mi.

12. Àwọn ènìyàn wọn yí ìsọ́ òru diọ̀sán; wọ́n ní, ìmọ́lẹ̀ súnmọ́ ibi tí òkùnkùn dé.

13. Bí mo tilẹ̀ ní ìrètí, ipò òku ní ilémi; mo ti tẹ́ ìbùsùn mi sínú òkùnkùn.

Jóòbù 17