Jóòbù 15:13-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Tí ìwọ fi yí ẹ̀mí rẹ padà lòdì síỌlọ́run, tí ó fi ń jẹ́ ki ọ̀rọ̀kọ́rọ̀kí ó máa bọ́ ní ẹnu rẹ̀ bẹ́ẹ̀?

14. “Kí ni ènìyàn tí ó fi mọ́? Àti ẹni tía tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo?

15. Kíyèsí i, òun (Ọlọ́run) kògbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀,àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀;

16. Ańbọ̀tórí ènìyàn, ẹni ìríra àtieléèérìí, tí ń mù ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mú omi.

17. “Èmi ó fihàn ọ́: gbọ́ ti èmi; Èyí tíèmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ,

18. tí àwọn ọlọ́gbọ́n ti pa ní ìtàn latiọ̀dọ̀ àwọn baba wọn wá, ti wọ́n kò sì fi pamọ́,

19. Àwọn tí a fi ilẹ̀ ayé fún nìkan,àlejò kan kò sì là wọ́n kọjá.

20. Ènìyàn búburú ń ṣe làálàá, pẹ̀lúìrora, ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo, àti iyeọdún ní a dá sílẹ̀ fún aninilára.

21. Ìró ìbẹ̀rù ń bẹ ní etí rẹ̀;nínú ìrora ni apanirun yóò dìde sí i.

22. O kò gbàgbọ́ pé òun ó jáde kúrònínú òkùnkùn; a sì ṣà á sápákan fún idà.

23. Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé,níbo ní ó wà? Ó mọ̀ pé ọjọ́òkùnkùn súnmọ́ tòsí.

24. Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú unbẹ̀rù, wọ́n ó sì sẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ímúra ogun.

25. Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdìsí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmáarè,

26. Ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn giga, àní fiìké kòóko àpáta rẹ̀ tí ó nipọn kọlù ú.

27. “Nítorí tí òun fi ọ̀rá rẹ̀ bo ara rẹ̀lojú, o sì ṣe jabajaba ọ̀rá sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.

Jóòbù 15