Jóòbù 11:4-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ìwọ sáà ti wí fún Ọlọ́run pé,‘ìṣe mi jẹ́ aláìléérí, èmi sì mọ́ ní óju rẹ.’

5. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ìbá jẹ́ sọ̀rọ̀,kí ó sì ya ẹnu rẹ̀ sí ọ lára;

6. Kí ó sì fi àsírí ọgbọ́n hàn ọ́ pé, ó pọ̀ ju òye ènìyàn lọ;Nítorí náà, mọ̀ pé Ọlọ́run tigbàgbé àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kan.

7. “Ìwọ ha le ṣe àwárí ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run bí?Ìwọ ha le ṣe àwárí ibi tí Olodùmáarè dé bi?

8. Ó ga ju àwọn ọ̀run lọ; kí ni ìwọ le è ṣe?Ó jìn ju jíjìn isà òkú lọ; kí ni ìwọ le mọ̀?

9. Ìwọ̀n rẹ̀ gùn ju ayé lọ,ó sì ní ibú ju òkun lọ.

Jóòbù 11