1. Ígbà náà ni Sófárì, ará Naamáa, dáhùn, ó sì wí pé:
2. “A ha lè ṣe kí a máa dáhùn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rọ̀?A ha lè fi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí da ènìyàn láre?
3. Ṣé àmọ̀tàn rẹ le mú ènìyàn pa ẹnu wọn mọ́ bí?Ṣé ẹnikẹ́ni kò ní bá ọ wí bí ìwọ bá yọ ṣùtì sí ni?
4. Ìwọ sáà ti wí fún Ọlọ́run pé,‘ìṣe mi jẹ́ aláìléérí, èmi sì mọ́ ní óju rẹ.’