Jóẹ́lì 3:9-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Ẹ kéde èyí ní àárin àwọn aláìkọlà;Ẹ dira ogun,ẹ jí àwọn alágbára,Jẹ kí awọn ajagun kí wọn bẹ̀rẹ̀ ogun,

10. Ẹ fi irin itulẹ yín rọ idà,àti dòjé yín rọ ọ̀kọ̀.Jẹ́ kí aláìlera wí pé,“Ara mi le koko.”

11. Ẹ wá kánkán, gbogbo ẹ̀yin aláìkọlà láti gbogbo àyíká,kí ẹ sì gbá ara yín jọ yí káàkiri:Níbẹ̀ ní kí o mú àwọn alágbára rẹ ṣọkalẹ̀, Olúwa.

12. “Ẹ jí, ẹ sì gòkè wá sí àfonífojìJéhóṣáfátì ẹ̀yin aláìkọlà:nítorí níbẹ̀ ní èmi yóò jòkòó láti ṣeìdájọ́ àwọn aláìkọlà yí kákìri.

13. Ẹ tẹ̀ dòjé bọ̀ ọ́,nítorí ìkórè pọ́n:ẹ wá, ẹ ṣọ̀kalẹ̀;nítorí ìfúntí kún, nítorí àwọnọpọ́n kún-à-kún-wọ́sílẹ̀nítorí ìwà búburú wọn pọ̀!”

Jóẹ́lì 3