Jóẹ́lì 3:7-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. “Kíyèsì í, èmi yóò gbé wọ́n dìde kúrò níbi tì ẹ̀yin ti tà wọ́n sí, èmi yóò sì san ẹ̀san ohun ti ẹ ṣe padà sórí ara yín.

8. Èmi yóò si tà àwọn ọmọkùnrin yín àti àwọn ọmọbìnrin yín sí ọwọ́ àwọn ọmọ Júdà, wọ́n yóò sì tà wọ́n fún àwọn ara Ṣábíà, fún orílẹ̀ èdè kan tí ó jìnnà réré.” Nítorí Olúwa ní o ti sọ ọ.

9. Ẹ kéde èyí ní àárin àwọn aláìkọlà;Ẹ dira ogun,ẹ jí àwọn alágbára,Jẹ kí awọn ajagun kí wọn bẹ̀rẹ̀ ogun,

10. Ẹ fi irin itulẹ yín rọ idà,àti dòjé yín rọ ọ̀kọ̀.Jẹ́ kí aláìlera wí pé,“Ara mi le koko.”

11. Ẹ wá kánkán, gbogbo ẹ̀yin aláìkọlà láti gbogbo àyíká,kí ẹ sì gbá ara yín jọ yí káàkiri:Níbẹ̀ ní kí o mú àwọn alágbára rẹ ṣọkalẹ̀, Olúwa.

12. “Ẹ jí, ẹ sì gòkè wá sí àfonífojìJéhóṣáfátì ẹ̀yin aláìkọlà:nítorí níbẹ̀ ní èmi yóò jòkòó láti ṣeìdájọ́ àwọn aláìkọlà yí kákìri.

13. Ẹ tẹ̀ dòjé bọ̀ ọ́,nítorí ìkórè pọ́n:ẹ wá, ẹ ṣọ̀kalẹ̀;nítorí ìfúntí kún, nítorí àwọnọpọ́n kún-à-kún-wọ́sílẹ̀nítorí ìwà búburú wọn pọ̀!”

14. Ọ̀pọ̀lọpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀ní àfonífojì ìdájọ́,nítorí ọjọ Olúwa kù si dẹ̀dẹ̀ní àfonífojì ìdájọ́.

15. Oòrùn àti òṣùpá yóò ṣú òkùnkùn,àti àwọn ìràwọ̀ kí yóò tan ìmọ́lẹ̀ wọn mọ́.

Jóẹ́lì 3