Jeremáyà 49:2-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,”ni Olúwa wí;“nígbà tí èmi yóò mú ìdágìrì ogun bá Rábàtí Ámónì yóò sì di òkítì ahoro,gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná.Nígbà náà ni Ísírẹ́lì yóòlé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,”ni Olúwa wí.

3. “Pohùnréré ẹkún ìwọ Hésíbónìnítorí Áì tí rún, kígbe jádeẹ̀yin ènìyàn Rábà, ẹ wọ aṣọọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀. Ẹ sárésókè sódò nínú ọgbà nítoríMákómù yóò lọ sí ìgbèkùnpẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.

4. Kí ló dé tí ẹ fi ń fi àfonífojì yín yangàn?Ẹ fi àfonífojì yín yangàn pẹ̀lú èṣo rere,ẹ̀yin ọmọbìnrin aláìsòótọ́.Gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé,‘ta ni yóò kò mí lójú?’

5. Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹláti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,”ni Olúwa wí:

Jeremáyà 49