Jeremáyà 48:23-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

23. sórí Kíríátaímù, Bẹti Gámù àti Bẹti Méónì,

24. sórí Kéríótì àti Bóásì,sórí gbogbo ìlú Móábù, nítòsí àti ní ọ̀nà jínjìn.

25. A gé ìwo Móábù kúrò,apá rẹ̀ dá,”ni Olúwa wí.

26. “Ẹ jẹ́ kí a mú u mutínítorí ó kó ìdọ̀tí bá Olúwa,jẹ́ kí Móábù pàfọ̀ nínú èébì rẹ̀,kí ó di ẹni ẹ̀gàn.

27. Ǹjẹ́ Ísírẹ́lì kò di ẹni ẹ̀gan rẹ?Ǹjẹ́ a kó o pẹ̀lú àwọn olètó bẹ́ẹ̀ tí o ń gbọn orí rẹ̀ pẹ̀lú yẹ̀yẹ́nígbákùúgbà bí a bá sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀?

28. Kúrò ní àwọn ìlú rẹ, kí o sì máa gbé láàrin àwọn òkúta,ẹ̀yin tí ó ti ń gbé inú ìlú Móábù.Ẹ dàbí i àdàbà tí ó kọ́ ìtẹ́ rẹ̀sí ẹnu ihò.

29. “A ti gbọ́ nípa ìgbéraga Móábù:àti ìwà mo gbọ́n tan rẹ̀àti ìgbéraga ọkàn rẹ̀.

Jeremáyà 48