Jeremáyà 42:17-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Nítorí náà, gbogbo àwọn tí ó ti pinnu láti ṣe àtìpó ní Éjíbítì ni yóò ti ipa idà kú, ìyàn àti àjàkálẹ̀-àrùn kò sì ní jẹ́ kí ẹníkẹ́ni nínú wọn yè tàbí sá àsálà nínú ibi tí èmi yóò mú wá sórí wọn.’

18. Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ ogun Ọlọ́run Ísírẹ́lì wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí èmi ti da ìbínú àti ìrunú síta sórí àwọn tí ó ń gbé ní Jérúsálẹ́mù, bẹ́ẹ̀ ni ìrunú mi yóò dà sita sórí yín, nígbà tí ẹ̀yin bá lọ sí Éjíbítì. Ẹ̀yin ó sì di ẹni ègún àti ẹní ẹ̀gàn àti ẹ̀sín, ẹ̀yin kì yóò sì rí ibí yìí mọ́.’

19. “Ẹ̀yin yóòkù Júdà, Olúwa ti sọ fún un yín pé, ‘Kí ẹ má ṣe lọ sí Éjíbítì.’ Ẹ mọ èyí dájú: Èmi kìlọ̀ fún un yín lónìí;

20. Pé àṣìṣe ńlá gbáà ni ẹ̀yin ṣe nígbà tí ẹ̀yin rán mi sí Olúwa Ọlọ́run yín pé, ‘Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa; sọ fún wa gbogbo ohun tí ó bá sọ, àwa yóò sì ṣe é.’

Jeremáyà 42