Jeremáyà 32:28-34 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

28. Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: Èmi ṣetan láti fi ìlú yìí fún àwọn ará Kálídéà àti fún Nebukadinésárì Ọba Bábílónì ẹni tí yóò kó o.

29. Àwọn ará Kálídéà tí ó ń gbógun tí ìlú yóò wọ ìlú. Wọn ó sì fi iná sí ìlú; wọn ó jó o palẹ̀ ní ọ̀nà ilé tí àwọn ènìyàn ti ń mú mi bínú, tí wọ́n ń rúbọ tùràrí lórí pẹpẹ fún Báálì ti wọn sì ń da ẹbọ òróró fún Ọlọ́run mìíràn.

30. “Àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì àti Júdà kò ṣe ohun kankan bí kò ṣe ibi lójúmi láti ìgbà èwe wọn. Nítorí àwọn ọmọ Isreli ti fi kìkì iṣẹ́ ọwọ́ wọ́n mú mi bínú ni Olúwa wí

31. Láti ọjọ́ tí wọ́n ti kọ́ ọ, títí di àkókò yìí ni ìlú yìí ti jẹ́ ohun ìbínú àti ìyọnu fún mi tó bẹ́ẹ̀ tí èmi yóò fà á tu kúrò níwájú mi.

32. Àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì àti àwọn ènìyàn Júdà ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ìbàjẹ́ ni wọn tí wọ́n ṣe. Àwọn Ísírẹ́lì, Ọba wọn àti gbogbo ìjòyè, àlùfáà àti wòlíì, àwọn ọkùnrin Júdà àti àwọn ènìyàn Jérúsálẹ́mù.

33. Wọ́n kọ ẹ̀yìn sími, wọ́n sì yí ojú wọn padà. Èmi kọ̀ wọ́n, síbẹ̀ wọn kò fetísílẹ̀ láti gbọ́ ẹ̀kọ́ tàbí kọbiara sí ìwà ìbàjẹ́.

34. Wọ́n kó òrìṣà ìríra wọn jọ sí inú ilé tí wọ́n fi orúkọ mi pè, wọ́n sì sọ́ di àìmọ́.

Jeremáyà 32