32. Èyí ni ohun tí Olúwa ọmọ ogun wí:“Wò ó! Ibi ń tànkálẹ̀ láti orílẹ̀ èdè kan sí òmíràn;Ìjì ńlá yóò sì ru sókè láti òpin ayé.”
33. Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò sọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.
34. Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkúnẹ̀yin olùsọ́ àgùntàn, ẹ yí nínú eruku,ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran,nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé,ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.