Jẹ́nẹ́sísì 49:17-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Dánì yóò jẹ́ ejo ni pópónààti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà,tí ó bu ẹsin jẹ ní ẹṣẹ̀,kí ẹni tí n gùn-un bá à le è subú sẹ́yìn.

18. “Mo ń dúró de ìtúsilẹ̀ rẹ, Olúwa

19. “Ẹgbẹ́-ogun àwọn ẹlẹ́sin yóò kọ lu Gádì,ṣùgbọ́n yóò kọ lu wọ́n ní gìgíṣẹ̀ wọn.

20. “Oúnjẹ Áṣérì yóò dára;yóò ṣe àṣè tí ó yẹ fún ọba.

21. “Náfútalì yóò jẹ́ abo àgbọ̀nríntí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ daradara.

22. “Jóṣẹ́fù jẹ́ àjàrà eléṣo,àjàrà eléṣo ní etí odò,tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.

Jẹ́nẹ́sísì 49