Jẹ́nẹ́sísì 30:40-43 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

40. Nígbà náà ni ó ya àwọn abo ẹran kúrò nínú agbo ẹran Lábánì, ó sì yà wọ́n sọ́tọ̀ kúrò lára àgbò, ó sì mú kí wọn máa gùn pẹ̀lú àwọn àgbò Jákọ́bù dúdú nìkan, bẹ́ẹ̀ ni ó kó agbo-ẹran jọ fún ara rẹ̀ láti ara agbo ẹran Lábánì.

41. Nígbà kígbà tí àwọn ẹran tí ó lera bá ń gùn, Jákọ́bù yóò fi àwọn ọ̀pá wọ̀nyí lélẹ̀ níwájú wọn, ní ibi tí wọn ti ń mumi.

42. Ṣùgbọ́n tí ó bá jẹ́ wí pé wọn kò lera, kò ní fi àwọn ọ̀pá náà lélẹ̀. Nítorí náà, àwọn tí kò lera ń jẹ́ ti Lábánì, nígbà tí àwọn tí ó lera ń jẹ́ ti Jákọ́bù.

43. Nítorí ìdí èyí, Jákọ́bù di ọlọ́rọ̀ gidigidi, agbo-ẹran rẹ̀ pọ̀ àti àwọn ìránṣẹ́-kùnrin, ìránṣẹ́-bìnrin pẹ̀lú ràkúnmí àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.

Jẹ́nẹ́sísì 30