Jẹ́nẹ́sísì 17:21-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú Ísáákì, ẹni tí Ṣárà yóò bí fún ọ ni ìwòyí àmọ́dún.”

22. Nígbà tí ó ti bá Ábúráhámù sọ̀rọ̀ tán, Ọlọ́run sì gòkè lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.

23. Ní ọjọ́ náà gan-an ni Ábúráhámù mú Ísímáélì ọmọ rẹ̀ àti àwọn ẹrú tí a bí ní ilé rẹ̀ àti àwọn tí ó fi owó rà, ó sì kọ wọ́n ní ilà. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì kọ gbogbo ọkùnrin tí ń bẹ ní ilé rẹ̀ ní ilà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa.

24. Ábúráhámù jẹ́ ẹni ọ̀kàndínlọ́gọ́rùnún (99) ọdún nígbà tí a kọ ọ́ ní ilà.

25. Ísímáélì ọmọ rẹ̀ jẹ́ ẹni ọdún mẹ́talá, (13).

26. Ábúráhámù pẹ̀lú rẹ̀ kọ ilà ní ọjọ́ náà gan-an.

27. Àti gbogbo ọkùnrin tí ó wà ní ilé Ábúráhámù, ìbá à ṣe èyí tí a bí ní ilé rẹ̀ tàbí èyí tí a fi owó rà lọ́wọ́ àlejò ni a kọ ní ílà pẹ̀lú rẹ̀.

Jẹ́nẹ́sísì 17