Jẹ́nẹ́sísì 10:21-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. A bí àwọn ọmọ fún Ṣémù tí Jáfétì jẹ́ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin: Ṣémù sì ni baba gbogbo àwọn ọmọ Ébérì.

22. Àwọn ọmọ Ṣémù ni:Élámù, Ásọ̀, Áfákísádì, Lúdì àti Árámù.

23. Àwọn ọmọ Árámù ni:Úsì, Úlì, Gétérì àti Méṣékì.

24. Áfákísádì ni baba Ṣélà,Ṣélà yìí sì ni ó bí Ébérì.

25. Ébérì sì bí ọmọ méjì:ọ̀kan sì ń jẹ́ Pélégì, nítorí ní ìgbà ayé rẹ̀ ni ilẹ̀ ayé pín sí oríṣìíríṣìí ẹ̀yà àti èdè. Orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Jókítanì.

26. Jókítanì sì bíÁlímádádì, Ṣéléfì, Hásámáfétì àti Jérà.

Jẹ́nẹ́sísì 10