Ísíkẹ́lì 36:34-38 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

34. ilẹ̀ ahoro náà ní àwa yóò tún kọ́ ti kì yóò wà ní ahoro lójú àwọn tí ó ń gba ibẹ̀ kọjá mọ́.

35. Wọn yóò sọ wí pé, “Ilẹ̀ yìí tí ó ti wà ní ṣíṣòfo tẹ́lẹ̀ ti dà bí ọgbà Édẹ́nì; àwọn ìlú tí ó wà ní wíwó lulẹ̀, ahoro tí a ti parun, ni àwa yóò mọdi sí tí yóò sì wà fún gbígbé ni ìsìnyí.”

36. Nígbà náà àwọn orílẹ̀ èdè tí ó wà ní àyíká yín tí ó kù yóò mọ̀ pé èmi Olúwa ti tún àwọn ohun tí ó bàjẹ́ kọ́, mo sì ti tún ohun tí ó di ìṣòfò gbìn. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, èmi yóò sì ṣe e?’

37. “Èyí yìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò yí sí ilé Ísírẹ́lì, èmi yóò sì ṣe èyí fún wọn. Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn yín pọ̀ lọ́pọ̀lọpọ̀ bí àgùntàn,

38. Kí ó pọ̀ lọ́pọ̀lọpọ̀ bí ọ̀wọ́ ẹran fún ìrúbọ ní Jérúsálẹ́mù ní àsìkò àjọ. Ìlú ti a parun yóò wá kún fún agbo àwọn ènìyàn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”

Ísíkẹ́lì 36