Ísíkẹ́lì 3:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Síwájú sí i, ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ ohun tí ó wà níwájú rẹ, jẹ ìwé tí a ká yìí; kí o sì lọ fi bá ilé Ísírẹ́lì sọ̀rọ̀.”

2. Mo sì ya ẹnu mi, ó sì mú mi jẹ ìwé kíká náà.

3. Ó tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ ìwe tí mo fún ọ yìí, fi bọ́ inú àti ikùn rẹ.” Nígbà náà ni mo jẹ ẹ́, dídùn rẹ̀ dàbí oyin ní ẹnu mi.

Ísíkẹ́lì 3