8. Pọ́ọ̀lù si wí tí ẹnu rẹ̀ pé, “Èmi kò ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀kẹ́ṣẹ̀ kan sì òfin àwọn Júù, tàbí tẹ́ḿpílì, tàbí sí Késárì”
9. Ṣùgbọ́n Fẹ́sítúsì ń fẹ́ láti ní ojúrere lọ́dọ̀ àwọn Júù, ó sì dá Pọ́ọ̀lù lóhùn, wí pe, “Ìwọ ń fẹ́ gòkè lọ sì Jerúsálémù, kí a sì ṣe ẹjọ́ nǹkan wọ̀nyí níbẹ̀ níwájú mi bí?”
10. Pọ́ọ̀lù sì wí pé, “Mo dúró níwájú ìtẹ́-ìdájọ́ Késárì níbi tí ó yẹ kí a ṣe ẹjọ́ mí: èmi kò ṣẹ àwọn Júù, bí ìwọ pẹ̀lú ti mọ̀ dájú.
11. Ǹjẹ́ bí mo bá ṣẹ̀, tí mo sí ṣe ohun kan tí ó yẹ fún ikú, èmi kò kọ̀ láti kú: ṣùgbọn bí kò bá sí otítọ́ kan nínú ẹ̀sùn tí àwọn Júù yìí fi mi sùn sí, ẹnìkan kò lẹ́tọ̀ọ́ láti fà mí lé wọn lọ́wọ́. Mo fí ọ̀ràn mi lọ Késárì.”