Hósíà 12:4-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ó bá ángẹ́lì ja ìjàkadì, ó sì borí rẹ̀Ó sunkún, ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ojú rere rẹ̀Ó bá Olúwa ní Bẹ́tẹ́lìÓ sì bá a sọ̀rọ̀ níbẹ̀,

5. àní Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun; Olúwa ni orúkọ ìrántí rẹ̀

6. Ṣùgbọ́n ìwọ́ gbọdọ̀ padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀;Di ìfẹ́ àti ìdájọ́ òdodo múkí ẹ sì dúró de Olúwa yín nígbà gbogbo.

7. Oníṣòwò ń lo òṣùnwọ̀n èkéÓ fẹ́ràn láti rẹ́nijẹ.

8. Éfúráímù gbéraga,“Èmi ní ìní fún ara mi, mo sì ti di ọlọ́rọ̀,pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ mi yìí, wọn kò le ká àìṣedéédéétàbí ẹ̀ṣẹ̀ kankan mọ́ mi lọ́wọ́”

Hósíà 12