Hágáì 2:17-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Mo fi ìrẹ̀dànù, ìmúwòdú àti yìnyín bá gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín jà; síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí ọ̀dọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.

18. ‘Láti òní lọ, láti ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹ́sàn-án, yìí kí ẹ kíyèsí, kí ẹ sì rò ó dáradára, ọjọ́ ti a fi ìpìlẹ̀ tẹ́ḿpìlì Olúwa lé lẹ̀, ròó dáradára:

19. Ǹjẹ́ èso ha wà nínú abà bí? Títí di àkókò yìí, àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ àti pómégíránátè, àti igi ólífì kò ì tíì so èso kankan.“ ‘Láti òní lọ ni èmi yóò bùkún fún-un yin.’ ”

20. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ Hágáì wá nígbà kejì, ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù náà pé:

Hágáì 2