8. Nígbà náà ni Hámánì sọ fún ọba Ṣérísésì pé, “Àwọn ènìyàn kan wà tí wọ́n fánká tí wọ́n sì túká ní ara àwọn ènìyàn ní gbogbo àgbáyé ìjọba rẹ̀ tí ìṣe wọn yàtọ̀ sí ti gbogbo àwọn tó kù tí wọn kò sì pa òfin ọba mọ́; èyí kì í ṣe ìfẹ́ ọba láti gbà fún wọn bẹ́ẹ̀.
9. Tí ó bá tẹ́ ọba lọ́rùn, kí a gbé òfin kan jáde tí yóò pa wọ́n run, èmi yóò sì fi ẹgbàarùn-ún talẹ́ńtì fàdákà sínú ìṣúra ọba fún àwọn ọkùnrin tí wọn ṣe iṣẹ́ náà.”
10. Nítorí náà ọba sì bọ́ òrùka dídán (èdìdì) tí ó wà ní ìka rẹ̀ ó sì fi fún Hámánì ọmọ Hámédátà, ará Ágágì, ọ̀ta àwọn Júù.