Ékísódù 34:8-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Mósè foríbalẹ̀ lẹ́ẹ̀kan náà ó sì sìn.

9. Ó wí pé, “Olúwa, bí èmi bá rí ojú rere rẹ, nígbà náà jẹ́ kí Olúwa lọ pẹ̀lú wa. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, ènìyàn ọlọ́rùn líle ni wọn, dárí búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wa jìn, kí o sì gbà wá gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ.”

10. Nígbà náà ni Olúwa wí pé: “Èmi dá májẹ̀mú kan pẹ̀lú yín. Níwájú gbogbo ènìyàn rẹ èmi yóò se ìyanu, tí a kò tí ì ṣe ní orílẹ̀ èdè ní gbogbo ayé rí. Àwọn ènìyàn tí ìwọ ń gbé láàrin wọn yóò rí i bí iṣẹ́ tí èmi Olúwa yóò ṣe fún ọ ti ní ẹ̀rù tó

11. Ṣe ohun tí èmi pa lásẹ fún ọ lónìí. Èmi lé àwọn ará Ámórì, àwọn ará Kénánì, àwọn ará Kítì àti àwọn ará Jébúsì jáde níwájú rẹ.

12. Má a sọ́ra kí o má ba à bá àwọn ti ó n gbé ilẹ náà tí ìwọ ń lọ dá májẹ̀mú, nítorí wọn yóò jẹ́ ìdíwọ́ láàrin rẹ.

13. Wó pẹpẹ wọn lulẹ̀, fọ́ òkúta mímọ́ wọn, kí o sì gé òpó Ásérè wọn. (Ère òrìsà wọn).

14. Ẹ má se sin ọlọ́rùn mìíràn, nítorí Olúwa, orúkọ ẹni ti ń jẹ́ òjòwú, Ọlọ́run owú ni.

Ékísódù 34