5. Nígbà náà ni ó rán àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Ísírẹ́lì, wọ́n sì rúbọ sísun, wọ́n fi ọ̀dọ́ màlúù rú ẹbọ àlàáfíà si Olúwa.
6. Mósè bu ìlàjì ẹ̀jẹ̀ ẹran sínú abọ́, ó sì fi ìlàjì tókù wọn ara pẹpẹ.
7. Nígbà náà ni ó sì mú ìwé májẹ̀mú, ó sì kà á sí àwọn ènìyàn. Wọ́n dáhùn pé, “Àwa yóò ṣe gbogbo ohun tí Olúwa wí: Àwa yóò sì gbọ́ràn.”
8. Nígbà náà ni Mósè gbé ẹ̀jẹ̀, ó sì wọn sí àwọn ènìyàn náà lára pé, “Èyí ni ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú tí Ọlọ́run ti ṣe pẹ̀lú yín ni ìbámu pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.”
9. Mósè àti Árónì, Nádábù àti Ábíhù àti àádọ́rin àwọn àgbààgbà Ísírẹ́lì gòkè lọ.
10. Wọ́n sì rí Ọlọ́run Ísírẹ́lì. Ní abẹ́ ẹṣẹ̀ rẹ̀ ni ohun kan bí i pèpéle ti a fi òkúta sáfírè ṣe wà. Èyí ti ó mọ́ niṣínniṣín bí àwọ̀ sánmọ̀ fúnraarẹ̀.
11. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí àwọn àgbààgbà Ísírẹ́lì wọ̀nyí; wọ́n ri Ọlọ́run, wọ́n jẹ, wọ́n sì mu.
12. Olúwa sì sọ fún Mósè pé, “Gòkè wá sí ọ̀dọ̀ mi, kí o sì dúró níhín-ín. Èmi yóò sì fún ọ ní òkúta ìkọ̀wé pẹ̀lú òfin àti ìlànà tí mo ti kọ sílẹ̀ fún ìtọ́sọ́nà wọn.”
13. Nígbà náà ni Mósè jáde lọ pẹ̀lú Jọsúà arákùnrin rẹ̀. Mósè lọ sí orí òkè Ọlọ́run.
14. Ó sì wí fún àwọn àgbààgbà pé, Ẹ dúró dè wá níhìn-ín yìí, títí àwa yóò fi tún padà tọ̀ yín wá, sì kíyèsìí, Árónì àti Húrì ń bẹ pẹ̀lú yín, bí ẹnikan bá ni ọ̀ràn kan, kí ó tọ̀ wọ́n lọ.
15. Nígbà tí Mósè gun orí òkè lọ, ìkúúkùù bo orí òkè náà.