4. Nígbà náà ni Mósè gbé ohùn rẹ̀ sókè sí Olúwa pé; “Kí ni kí èmi kí ó ṣe fún àwọn ènìyàn yìí? Wọ́n múra tan láti sọ mi ni òkúta.”
5. Olúwa sì dá Mósè lóhùn pé, “Má a lọ ṣíwájú àwọn ènìyàn, mú nínú àwọn àgbààgbà Ísírẹ́lì pẹ̀lú rẹ, mú ọ̀pá tí ìwọ fi lu odò Náìlì lọ́wọ́ kí ó sì máa lọ.
6. Èmi yóò dúró ni ibẹ̀ dè ọ ni orí àpáta ni Hórébù. Ìwọ ó sì lu àpáta, omi yóò sì jáde nínú rẹ̀ fún àwọn ènìyàn láti mu.” Mósè sì se bẹ́ẹ̀ ni iwájú àwọn àgbààgbà Ísírẹ́lì.
7. Ó sì sọ orúkọ ibẹ̀ ni Másá (ìdánwò) àti Méríba (kíkùn) nítorí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sọ̀, wọ́n sì dán Olúwa wò, wọ́n wí pé, “Ǹjẹ́ Olúwa ń bẹ láàrin wa tàbí kò sí?”
8. Àwọn ara Ámélékì jáde, wọ́n sì dìde ogun sí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ni Réfídímù.