1. Olúwa sọ fún Mósè pé,
2. “Ẹ ya àwọn àkọ́bí yín ọkùnrin ṣọ́tọ̀ fún mi. Èyí ti ó bá jẹ́ àkọ́bí láàrin àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jẹ́ tèmi, ìbáà ṣe ènìyàn tàbí ẹranko.”
3. Nígbà náà ni Mósè sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ rántí ọjọ́ òní, ọjọ́ ti ẹ jáde kúrò ni ilẹ́ Éjíbítì, kúrò ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin ti ń ṣe ẹrú, nítorí Olúwa mú un yín jáde kúrò ni inú rẹ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára. Ẹ má se jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú.