Ékísódù 12:45-51 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

45. Ṣùgbọ́n àlejò àti alágbàṣe kò ni jẹ nínú rẹ̀.

46. “Nínú ilé ni ẹ ti gbọdọ̀ jẹ ẹ́; ẹ kò gbọdọ̀ mú èyíkéyìí nínú ẹran náà jáde kúrò nínú ilé. Ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan nínú egungun rẹ̀.

47. Gbogbo àjọ Ísírẹ́lì ni ó gbọdọ̀ ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀.

48. “Àjòjì ti ó bá ń gbé ní àárin yín ti ó bá fẹ́ kópa nínú àjọ ìrékọjá Olúwa, ni o gbọdọ̀ kọ gbogbo àwọn ọmọkùnrin ilé rẹ̀ ní ìlà; ní ìgbà náà ni ó lè kó ipa gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ tí a bí ní ilẹ̀ náà. Gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí a kò bá kọ ní ìlà, wọ́n kò ni jẹ ni ara rẹ̀.

49. Òfin yìí kan náà ni ó mú àwọn ọmọ tí a bí ni ilẹ̀ náà àti àwọn àlejò tí ń gbé ní àárin yín.”

50. Gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mósè àti Árónì.

51. Àti pé ní ọjọ́ náà gan-an ni Olúwa mú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jáde kúrò ní ilẹ̀ Éjíbítì gẹ́gẹ́ bí ìpín ìpín wọn.

Ékísódù 12