Deutarónómì 8:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ẹ kíyèsí láti máa tẹ̀lé gbogbo àṣẹ tí mo fún un yín lónìí, kí ẹ báà le yè kí ẹ sì pọ̀ sí i wọ ilẹ̀ náà, kí ẹ sì le gba ilẹ̀ náà, tí Olúwa fìbúra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá a yín.

2. Ẹ rántí bí Olúwa Ọlọ́run yín ti tọ́ ọ yín sọ́nà ní gbogbo ọ̀nà ní ihà fún ogójì ọdún wọ̀nyí láti tẹ orí i yín ba àti láti dán an yín wò kí ó báà le mọ bí ọkàn yín ti rí, bóyá ẹ ó pa òfin rẹ̀ mọ́ tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.

3. Ó rẹ̀ yín sílẹ̀ nípa fífi ebi pa yín, Ó sì fi mánà bọ́ ọ yín, èyí tí ẹ kò mọ̀, tí àwọn baba yín kò mọ̀, kí ó báà lè kọ́ ọ yín pé, ènìyàn kò wà láàyè nípa oúnjẹ nìkan, bí kò ṣe ohun gbogbo tí ó jáde láti ẹnu Olúwa wá.

4. Aṣọ yín kò gbó mọ́ ọ yín lọ́rùn bẹ́ẹ̀ ní ẹṣẹ̀ yín kò sì wú, ní ogójì ọdún náà.

5. Ẹ mọ̀ ní ọkàn an yín pé, bí baba ti ń kọ́ ọmọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín ń kọ́ ọ yín.

6. Torí èyí, ẹ gbọdọ̀ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́, nípa rínrìn ní ọ̀nà rẹ̀, àti bíbẹ̀rù rẹ̀.

Deutarónómì 8