15. Ẹ rántí pé ẹ ti jẹ́ ẹrú ní Éjíbítì rí, àti pé Olúwa Ọlọ́run yín yọ yín kúrò níbẹ̀ pẹ̀lú agbára ńlá, àti nína ọwọ́ rẹ̀. Torí èyí ni Olúwa Ọlọ́run yín ṣe pàṣẹ fún un yín láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́.
16. “Bọ̀wọ̀ fún baba àti ìyáà rẹ, bí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín, kí ẹ ba à le è pẹ́ láyé, àti kí ó bá à lè dára fún un yín ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín.
17. “Má ṣe pànìyàn.
18. “Má ṣe ṣe panṣágà.
19. “Má ṣe jalè.
20. “Má ṣe jẹ́rìí èké sí aládùúgbò rẹ
21. “Má ṣe ṣe ojúkòkòrò sí aya aládúgbò rẹ, má ṣe ṣe ojúkòkòrò sí ilé tàbí ilẹ̀ alábágbé rẹ, sí ẹrúkùnrin tàbí ẹrúbìnrin rẹ̀, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, tàbí ohunkóhun tí í ṣe ti aládúgbò rẹ.”
22. Wọ̀nyí ni àwọn àṣẹ Olúwa tí a kéde rẹ̀ sí gbogbo ìpéjọpọ̀ ọ yín, níbẹ̀ ní orí òkè, láàrin iná, ìkùukù àti òkùnkùn biribiri: Kò sì fi ohunkóhun kún un mọ́. Ó sì kọ wọ́n sínú sílétì méjì, Ó sì fi wọ́n lé mi lọ́wọ́.
23. Nígbà tí ẹ gbóhùn láti inú òkùnkùn wá, nígbà tí iná náà ń yọná lala, àwọn aṣáájú ẹ̀yà a yín àti àwọn alàgbà a yín tọ̀ mí wá.