Deutarónómì 34:10-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Láti ìgbà náà kò sì sí wòlíì tí ó dìde ní Ísírẹ́lì bí i Móṣè, ẹni tí Olúwa mọ̀ lójúkojú,

11. tí ó ṣe gbogbo iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu tí Olúwa rán an láti lọ ṣe ní Éjíbítì sí Fáráò àti sí gbogbo àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ àti sí gbogbo ilẹ̀ náà.

12. Nítorí kò sí ẹni tí ó tíì fi gbogbo ọ̀rọ̀ agbára hàn, tàbí ṣe gbogbo ẹ̀rù ńlá tí Móṣè fi hàn ní ojú gbogbo Ísírẹ́lì.

Deutarónómì 34