Àwọn Hébérù 11:6-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Ṣùgbọ́n làísí ìgbàgbọ́ kò ṣeéṣe láti wù ú; nítorí ẹni tí ó bá ń tọ Ọlọ́run wá kò lè sàì gbàgbọ́ pé o ń bẹ, àti pé òun ní olùṣẹ̀san fún àwọn tí o fi ara balẹ̀ wá a.

7. Nípa ìgbàgbọ́ ni Nóàh, nígbà ti Ọlọ́run, kìlọ̀ ohun tí a kóò tíì rí fún un, o bẹ̀rù Ọlọ́run ó sì kan ọkọ̀ fún ìgbàlà ilé rẹ̀, nípa èyí tí ó da ayé lẹ̀bí, ó sì di ajogún òdodo tí i ṣe nípa ìgbàgbọ́.

8. Nípa ìgbàgbọ́ ní Ábúráhámù, nígbà tí a ti pé e láti jáde lọ sí ibi tí òun yóò gbà fún ilẹ̀ ìní, ó gbọ́, ó sì jáde lọ, láì mọ ibi tí òun ń rè.

9. Nípa ìgbàgbọ́ ní o ṣe àtìpó ní ilẹ̀ ìlérí, bí ẹni pé ni ilẹ̀ àjèjì, o ń gbé inú àgọ́, pẹ̀lú Ísáákì àti Jákọ́bù, àwọn ajogún ìlérí kan náà pẹ̀lú rẹ̀:

10. Nítorí tí ó ń rétí ìlú tí ó ní ìpìlẹ̀; ọ èyí tí Ọlọ́run tẹ̀dó tí o si kọ́.

11. Nípa ìgbàgbọ́ ni Sárà tìkararẹ̀ pẹ̀lú fi gba agbára láti lóyún, nígbà tí ó kọja ìgbà rẹ̀, nítorí tí o ka ẹni tí o ṣe ìlérì sí olootọ́.

Àwọn Hébérù 11