Àwọn Hébérù 10:6-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Ẹbọ sísun àti ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ niìwọ kò ní inú dídùn sí.

7. Nígbà náà ni mo wí pé, ‘Kíyèsí i (nínú ìwé kíká ni a gbé kọọ́ nípa ti èmi)mo dé láti ṣe ìfẹ́ rẹ, Ọlọ́run.’ ”

8. Nígbà tí o wí ni ìṣáajú pé, “Ìwọ kò fẹ́ ẹbọ àti ọ̀rẹ àti ẹbọ sísun, àti ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò ni inú dídùn si wọn” (àwọn èyí tí a ń rú gẹ́gẹ́ bí òfin).

9. Nígbà náà ni ó wí pé, “Kíyèsí i, mo de láti ṣe ìfẹ́ rẹ Ọlọ́run.” O mu ti ìṣáaju kúrò, kí a lè fi ìdí èkejì múlẹ̀.

10. Nípa ìfẹ́ náà ni a ti sọ wá di mímọ́ nípa ẹbọ ti Jésù Kírísítì fi ara rẹ̀ rú lẹ̀ẹ̀kanṣoṣo.

11. Àti olukulùkù àlùfáà sì ń dúró lójoojúmọ́ láti ṣiṣẹ́ ìsìn, ó sì ń ṣe ẹbọ kan náà nígbàkúgbà, tí kò lè mú ẹ̀ṣẹ̀ kúrò láé:

12. Ṣùgbọ́n òun, lẹ̀yìn ìgbà tí o ti rú ẹbọ kan fún ẹ̀ṣẹ̀ títí láé, o jòkòó lọ́wọ́ ọ̀tún Ọlọ́run;

13. Láti ìgbà náà, ó rétí títí a o fi àwọn ọ̀ta rẹ̀ ṣe àpótí itísẹ̀ rẹ̀.

14. Nítorí nípa ẹbọ kan a ti mú àwọn tí a sọ di mímọ́ pé títí láé.

15. Ẹ̀mí mímọ́ sì ń jẹri fún wa pẹ̀lú: Nítorí lẹ̀yìn tí ó wí pé,

Àwọn Hébérù 10