7. Nítòótọ́ Olúwa Ọlọ́run kò ṣe ohun kanláìfi èrò rẹ̀ hànsí àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
8. Kìnnìún ti bú ramúramùta ni kì yóò bẹ̀rù? Olúwa Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ta ni le ṣe àìsọtẹ́lẹ̀?
9. Ẹ kéde ní ààfin Áṣídódùàti ní ààfin ní ilẹ̀ Éjíbítì.“Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samáríà;Kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrin rẹ̀àti ìnílára láàrin àwọn ènìyàn rẹ.”
10. “Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí,“Ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”
11. Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run wí:“Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run;yóò wó ibi gíga yín palẹ̀a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”