Àìsáyà 59:5-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Wọn ń pa ẹyín pamọ́lẹ̀wọn sì ń ta owú aláǹtakùn.Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹyin wọn yóò kú,àti nígbà tí a pa ọ̀kan, pamọ́lẹ̀ ni ó jáde.

6. Òwú wọn kò wúlò fún aṣọ rírán;wọn kò lè fi aṣọ tí wọ́n hun bo ara wọn.Iṣẹ́ wọn jẹ́ ti ibi, ìwà jàǹdàkú sì kún ọwọ́ wọn.

7. Ẹsẹ̀ wọn yára bọ́ sínú ẹ̀ṣẹ̀;wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀.Èrò wọn sì jẹ́ èrò ibi;ìparun àti ìdahoro ni ó wà ní ṣíṣe àmì ọ̀nà wọn.

Àìsáyà 59