7. Nínú ìpọ́njú mi, èmi ké pé Olúwa,èmi sì gbé ohùn mi sókè sí Ọlọ́run mi.Ó sí gbóhùn mi láti tẹ́ḿpìlì rẹ̀igbe mí wọ etí rẹ̀.
8. “Ilẹ̀ sì mì, ó sì wárìrì;ìpìlẹ̀ ọ̀run wárìrì,ó sì mì, nítorí tí ó bínú.
9. Èéfín sì jáde láti ihò-imú rẹ̀ wá;iná láti ẹnu rẹ̀ wá,ó sì ń jónirun, ẹ̀yín sì ń ràn nípasẹ rẹ̀.
10. Ó tẹ orí ọ̀run ba pẹ̀lú, ó sì sọ̀kalẹ̀;òkùnkùn biribiri sì ń bẹ ní àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
11. Ó sì gun orí kérúbù, ó sì fò:a sì rí i lórí ìyẹ́ afẹ́fẹ́.
12. Ó sì fi òkùnkùn ṣe ibùjókòó yí ara rẹ̀, àti àgbájọ omi,àní ìsúdudu ìkùukùu àwọ̀n sánmà.
13. Nípaṣẹ̀ ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀ẹ̀yín-iná ràn.