32. Ó sì ṣe, Dáfídì dé orí òkè, níbi tí ó gbé wólẹ̀ sin Ọlọ́run, sì wò ó, Húsáì ará Áríkà sì wá láti pàdé rẹ̀ pẹ̀lú aṣọ rẹ̀ yíya, àti erùpẹ̀, lórí rẹ̀.
33. Dáfídì sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá bá mi kọjá, ìwọ ó sì jẹ́ ìdíwọ́ fún mi.
34. Bí ìwọ bá sì padà sí ìlú, tí o sì wí fún Ábúsálómù pé, ‘Èmi ó ṣe ìránṣẹ́ rẹ ọba, gẹ́gẹ́ bí èmi ti ṣe ìránṣẹ́ baba rẹ nígbà àtíjọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó sì jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ nísínsinyìí,’ kí ìwọ sì bá ìmọ̀ Áhítófélì jẹ́.
35. Ṣé Sádókù àti Ábíátarì àwọn àlùfáà wà níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀? Yóò sì ṣe, ohunkóhùn tí ìwọ bá gbọ́ láti ilé ọba wá, ìwọ ó sì sọ fún Sádókù àti Ábíátarì àwọn àlùfáà.
36. Wò ó, àwọn ọmọ wọn méjèèjì sì wà níbẹ̀ pẹ̀lú wọn, Áhímásì ọmọ Sádókù, àti Jónátánì ọmọ Ábíátárì; láti ọwọ́ wọn ni ẹ̀yín ó sì rán ohùnkóhun tí ẹ̀yín bá gbọ́ sí mi.”
37. Húsáì ọ̀rẹ́ Dáfídì sì wá sí ìlú, Ábúsálómù sì wá sí Jérúsálẹ́mù.