2 Ọba 3:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Jéhórámù ọmọ Áhábù ó sì di ọba Ísírẹ́lì ní Ṣamáríà ní ọdún kejìdínlógún ti Jéhósáfátì ọba Júdà, ó sì jọba fún ọdún méjìlá.

2. Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí ti ìyá àti bàbá rẹ̀ ti ṣe. Ó gbé òkúta ère ti Báálì tí baba rẹ̀ ti ṣe.

3. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó fi ara mọ́ ẹ̀ṣẹ̀ Jéróbóámù ọmọ Nébátì, tí ó ti fi Ísírẹ́lì bú láti dẹ́ṣẹ̀; kò sì yí kúrò lọ́dọ̀ wọn.

4. Nísinsìn yìí Mésà ọba Móábù ń sin àgùntàn, ó sì gbọdọ̀ fi fún ọba Ísírẹ́lì pẹ̀lú ọgọ́rún ẹgbẹ̀rùnún ọ̀dọ́ àgùntàn àti pẹ̀lú irú ọgọ́runún ẹgbẹ̀rúnún (hundred thousand) àgbò.

2 Ọba 3