2 Ọba 22:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Jòsáyà jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó di ọba, ó sì jọba ní Jérúsálẹ́mù fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jédídà ọmọbìnrin Ádáyà; ó wá láti Bósíkátì.

2. Ó sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Dáfídì bàbá a rẹ̀, kò sì yípadà sí apá ọ̀tún tàbí sí apá òsì.

3. Ní ọdún kejìdínlógún tí ó fi jọba. Ọba Jòsáyà rán akọ̀wé, Ṣáfánì ọmọ Ásálíà, ọmọ Mésúlámù, sí ilé Olúwa. Ó wí pé;

2 Ọba 22