2 Ọba 21:23-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

23. Àwọn ìránṣẹ́ Ámónì dìtẹ̀ lórí rẹ̀ wọ́n sì lu ọba pa ní àárin ilé rẹ̀.

24. Nígbà náà àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà pa gbogbo àwọn tí ó dìtẹ̀ sí ọba Ámónì, wọ́n sì fi Jòsíáyà ọmọ rẹ̀ jọba ní àyè rẹ̀.

25. Àti gẹ́gẹ́ bí ìyókù iṣẹ́ ti ìjọba Ámónì àti ohun tí ó ṣe, ṣé wọn kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn àwọn ọba Júdà?

26. Wọ́n sì sin ín sínú isà òkú nínú ọgbà Úṣà. Jòṣíáyà ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.

2 Ọba 21