2 Ọba 20:12-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Ní àkókò náà ni Méródákì-Báládánì ọmọ Báládánì ọba Bábílónì rán ṣẹ́ ìwé àti ẹ̀bùn sí Heṣekáyà nítorí tí ó ti gbọ́ nípa àìsàn Heṣekáyà.

13. Heṣekáyà gba ìránṣẹ́ náà ó sì fi hàn wọ́n, gbogbo ohun tí ó wà nínú ilé ìṣúra—sílífà, àti wúrà, àti tùràrí, àti òróró dáradára àti Ìhámọ́ra àti gbogbo èyí tí a rí lára ìṣúra rẹ̀. Kò sí nǹkan nínú ààfin rẹ̀ tàbí nínú gbogbo ìjọba rẹ̀ tí Heṣekáyà kò sì fi hàn wọ́n.

14. Nígbà náà Àìṣáyà wòlíì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Heṣekáyà ó sì béèrè pé, “Kí ni àwọn ọkùnrin náà sọ, àti níbo ni wọ́n ti ń bọ̀ wá?”“Lati ìlú jínjìn réré,” Hesekíáyà dáhùn. “Wọ́n wá láti Bábílónì.”

15. Wòlíì náà béèrè pé, “Kí ni wọ́n rí ní ààfin rẹ?”“Wọ́n rí gbogbo nǹkan ní ààfin mi,” Heṣekáyà wí pé. “Kò sí nǹkankan lára àwọn ìṣúra tí èmi kò fi hàn wọ́n.”

16. Nígbà náà Àìsáyà wí fún Heṣekáyà pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa:

2 Ọba 20