18. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì bínú gídígídí pẹ̀lú Ísírẹ́lì ó sì mú wọn kúrò níwájú rẹ̀. Èyà Júdà nìkan ṣoṣo ni ó kù,
19. Àti pẹ̀lú, Júdà kò pa òfin Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Wọ́n tẹ̀lé ìhùwàsí àwọn Ísírẹ́lì tí wọ́n ṣe.
20. Nítorí náà Olúwa kọ gbogbo àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì; ó sì jẹ wọ́n níyà. Ó sì fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn olè tí tí tí ó fi ta wọ́n nù kúrò níwájú rẹ̀.
21. Nígbà tí ó ta Ísírẹ́lì kúrò láti ìdílé Dáfídì, wọ́n sì mú Jéróbámù ọmọ Nébátì jẹ ọba wọn. Jéróbóámù sì mú kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì yípadà kúrò ní tí tẹ̀lé Olúwa, ó sí mú kí wọn dẹ́sẹ̀ ńlá.
22. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì forítìí nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ Jéróbámù kò sì yí padà kúrò lọ́dọ̀ wọn